1 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, nítorí pé ó ṣeun,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé,“Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”
3 Kí àwọn ará ilé Aaroni wí pé,“Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”
4 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù OLUWA wí pé,“Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”
5 Ninu ìpọ́njú, mo ké pe OLUWA,ó dá mi lóhùn, ó sì tú mi sílẹ̀.
6 Nígbà tí OLUWA wà pẹlu mi, ẹ̀rù kò bà mí.Kí ni eniyan lè fi mí ṣe?