4 àwọn tí ń wí pé,“Ẹnu wa yìí ni a óo fi ṣẹgun,àwa la ni ẹnu wa; ta ni ó lè mú wa?”
5 OLUWA wí pé, “Nítorí ìnira àwọn aláìṣẹ̀,ati nítorí ìkérora àwọn tí à ń pọ́n lójú,n óo dìde nisinsinyii,n óo sì dáàbò bò wọ́n bí ọkàn wọn ti ń fẹ́.”
6 Ìlérí tó dájú ni ìlérí OLUWA,ó dàbí fadaka tí a yọ́ ninu iná ìléru amọ̀,tí a dà ninu iná nígbà meje.
7 Dáàbò bò wá, OLUWA, pa wá mọ́ laelaekúrò lọ́wọ́ irú àwọn eniyan báwọ̀nyí.
8 Àwọn eniyan burúkú ń yan kiri,níwọ̀n ìgbà tí àwọn eniyan ń ṣe àpọ́nlé iṣẹ́ ibi.