4 “Ìbànújẹ́ àwọn tí ń sá tọ ọlọrun mìíràn lẹ́yìn yóo pọ̀:Èmi kò ní bá wọn ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ fún ìrúbọ,bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kò ní gbọ́ orúkọ wọn lẹ́nu mi.”
5 OLUWA, ìwọ ni ìpín mi, ìwọ ni mo yàn;ìwọ ni ò ń jẹ́ kí ọ̀ràn mi fìdí múlẹ̀.
6 Ìpín tí ó bọ́ sí mi lọ́wọ́ dára pupọ;ogún rere ni ogún ti mo jẹ.
7 Èmi óo máa yin OLUWA, ẹni tí ó ń fún mi ní òye;ọkàn mi ó sì máa tọ́ mi sọ́nà ní òròòru.
8 Mò ń wo OLUWA ní iwájú mi nígbà gbogbo,nítorí pé Ọlọrun dúró tì mí, ẹsẹ̀ mi kò ní yẹ̀.
9 Nítorí náà ni ọkàn mi ṣe ń yọ̀, tí inú mi dùn;ara sì rọ̀ mí.
10 Nítorí o kò ní gbàgbé mi sí ipò òkú,bẹ́ẹ̀ ni o kò ní jẹ́ kí ẹni tí ó fi tọkàntọkàn sìn ọ́ rí ìdíbàjẹ́.