3 Ìhàlẹ̀ ọ̀tá bà mí ninu jẹ́,nítorí ìnilára àwọn eniyan burúkú;wọ́n kó ìyọnu bá mi,wọ́n ń bínú mi, inú wọn sì dùn láti máa bá mi ṣọ̀tá.
4 Ọkàn mi wà ninu ìrora,ìpayà ikú ti dé bá mi.
5 Ẹ̀rù ati ìwárìrì dà bò mí,ìpayà sì bò mí mọ́lẹ̀.
6 Mo ní, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà!Ǹ bá fò lọ, ǹ bá lọ sinmi.
7 Áà! Ǹ bá lọ jìnnà réré,kí n lọ máa gbé inú ijù;
8 ǹ bá yára lọ wá ibi ààbòkúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́ líle ati ìjì.”
9 Da èrò wọn rú, OLUWA,kí o sì dà wọ́n lédè rú;nítorí ìwà ipá ati asọ̀ pọ̀ ninu ìlú.