6 Ọlọrun, olùpèsè ibùjókòó fún àlejò tí ó nìkan wà;ẹni tí ó kó àwọn ẹlẹ́wọ̀n jáde sinu ìdẹ̀ra,ṣugbọn ó sì fi àwọn ọlọ̀tẹ̀ sílẹ̀ ninu ilẹ̀ gbígbẹ.
7 Ọlọrun, nígbà tí ò ń jáde lọ níwájú àwọn eniyan rẹ,nígbà tí ò ń yan la aṣálẹ̀ já,
8 ilẹ̀ mì tìtì, ọ̀run pàápàá rọ òjò,níwájú Ọlọrun, Ọlọrun Sinai,àní, níwájú Ọlọrun Israẹli.
9 Ọlọrun, ọpọlọpọ ni òjò tí o rọ̀ sílẹ̀;o sì mú ilẹ̀ ìní rẹ tí ó ti gbẹ pada bọ̀ sípò.
10 Àwọn eniyan rẹ rí ibùgbé lórí rẹ̀;Ọlọrun, ninu oore ọwọ́ rẹ, o pèsè fún àwọn aláìní.
11 OLUWA fọhùn,ogunlọ́gọ̀ sì ni àwọn tí ó kéde ọ̀rọ̀ rẹ̀.
12 Gbogbo àwọn ọba ni ó sá tàwọn tọmọ ogun wọn;àwọn obinrin tí ó wà nílé,