2 Jẹ́ kí adura mi dé ọ̀dọ̀ rẹ;tẹ́tí sí igbe mi.
3 Nítorí pé ọkàn mi kún fún ìyọnu;mo sì súnmọ́ isà òkú.
4 Mo dàbí àwọn tí ó ń wọ ibojì lọ;mo dà bí ẹni tí kò lágbára mọ.
5 N kò yàtọ̀ sí ẹni tí a pa tì sí apá kan láàrin àwọn òkú,mo dàbí ẹni tí a pa, tí ó sùn ninu ibojì,bí àwọn tí ìwọ kò ranti mọ́,nítorí pé wọ́n ti kúrò lábẹ́ ìtọ́jú rẹ.
6 O ti fi mí sinu isà òkú tí ó jìn pupọ,ninu òkùnkùn, àní ninu ọ̀gbun.
7 Ọwọ́ ibinu rẹ wúwo lára mi,ìgbì ìrúnú rẹ sì bò mí mọ́lẹ̀.
8 O ti mú kí àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi fi mí sílẹ̀;mo sì ti di ẹni ìríra lọ́dọ̀ wọn:mo wà ninu àhámọ́, n kò sì lè jáde;