11 Mo ti fi ojú mi rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi,mo sì ti fi etí mi gbọ́ ìparun àwọn ẹni ibi tí ó gbé ìjà kò mí.
12 Àwọn olódodo yóo gbilẹ̀ bí igi ọ̀pẹ,wọn óo dàgbà bí igi kedari ti Lẹbanoni.
13 Wọ́n dàbí igi tí a gbìn sí ilé OLUWA,tí ó sì ń dàgbà ninu àgbàlá Ọlọrun wa.
14 Wọn á máa so èso títí di ọjọ́ ogbó wọn,wọn á máa lómi lára, ewé wọn á sì máa tutù nígbà gbogbo;
15 láti fihàn pé olóòótọ́ ni OLUWA;òun ni àpáta mi, kò sì sí aiṣododo lọ́wọ́ rẹ̀.