6 Mose ati Aaroni wà lára àwọn alufaa rẹ̀;Samuẹli pàápàá wà lára àwọn tí ń pe orúkọ rẹ̀;wọ́n ké pe OLUWA ó sì dá wọn lóhùn.
7 Ó bá wọn sọ̀rọ̀ ninu ọ̀wọ̀n ìkùukùu;wọ́n pa òfin rẹ̀ mọ́;wọ́n sì tẹ̀lé ìlànà tí ó fún wọn.
8 OLUWA Ọlọrun wa, o dá wọn lóhùn;Ọlọrun tíí dáríjì ni ni o jẹ́ fún wọn;ṣugbọn ó gbẹ̀san ìwàkiwà wọn.
9 Ẹ yin OLUWA, Ọlọrun wa,kí ẹ sì jọ́sìn níbi òkè mímọ́ rẹ̀;nítorí pé mímọ́ ni OLUWA Ọlọrun wa.