17 Ó sì rán ọkùnrin kan ṣíwájú wọnJósẹ́fù tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Wọn fi sẹkẹ́sẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ Rẹ̀a gbé ọrùn Rẹ̀ sínú irin
19 Títí ọ̀rọ̀ tí ó sọ tẹ́lẹ̀ fi ṣẹtítí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Ọba ránsẹ́ lọ tú u sílẹ̀àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ Rẹ̀aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 Gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Rẹ̀, kí ó máaṣe àkóso àwọn ọmọ aládékí ó sì kọ́ àwọn àgbà Rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Ísírẹ́lì wá sí Éjíbítì;Jákọ́bù sì ṣe àtìpó ní ilé Ámù.