Sáàmù 35 BMY

Àdúrà Fún Ìrànlọ́wọ́ Kúrò Lọ́wọ́ Ọ̀tá

1 Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbógun tì mí;kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!

2 Di aṣà àti àpáta mú,kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!

3 Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi;sọ fún ọkàn mi pé, “Èmi ni ìgbàlà Rẹ.”

4 Kí wọn kí ó dààmú, kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú:kí a sì mú wọn padà,kí a sì dààmú àwọn tí ń gbérò ìpalára mi.

5 Jẹ́ kí wọn dà bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,kí ángẹ́lì Olúwakí ó máa lé wọn kiri.

6 Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó sókùnkùnkí ó sì máa yọ́,kí áńgẹ́lì Olúwakí ó máa lépa wọn!

7 Nítorí pé, ní àìnídìí ní wọ́n dẹàwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtòfún ọkàn mi.

8 Jẹ́ kí ìparun kí ó wá síorí wọn lójijì.Àwọ̀n Rẹ̀ tí ó dẹ pamọ́,kí ó mú àwọn tìkálára wọn;kí wọn ṣubú sínú kòtòsí ìparun ara Rẹ̀.

9 Nígbà náà ni ọkàn miyóò yọ̀ nínú Olúwa,àní ayọ̀ ńlá nínú ìgbàlà Rẹ̀.

10 Gbogbo egúngún mi yóò wí pé,“ìwọ Olúwa,ta ni ó dà bí i Rẹ̀?O gba talákà làlọ́wọ́ àwọn tí ó lágbárajù wọ́n lọ,talákà àti aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”

11 Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;wọ́n bi mi léèrè àwọn ohuntí èmi kò mọ̀.

12 Wọ́n fi búburú san ire fún mi;láti sọ ọkàn mi di òfo.

13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni,nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn,mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;mo fi ààwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríbaní oókan àyà mi;

14 bí i ẹni wí pé ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́nmi ní wọ́n;mo ń lọọ́ kiri bí ẹni tíń sọ̀fọ̀ fún ìyà Rẹ̀,tí o tẹríba nínú ìbànújẹ́.

15 Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ miwọ́n kó ara wọn jọ wọ́n sì yọ̀,wọ́n kó ara wọn jọ sí mi;àní àwọn tí èmi kò mọ̀wọ́n fà mí yawọ́n kò sì dákẹ́.

16 Àwọn àgàbàgebè ń ṣe yẹ̀yẹ́mi ṣíwájú àti sí wájú síiwọ́n pa eyín wọnkeke sí mi.

17 Yóò ti pẹ́tó,ìwọ Olúwa,tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?Yọ mí kúrò nínú ìparun wọnàní ẹ̀mí i mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.

18 Nígbà náà ni èmi yóò sọpẹ́ fún Ọnínú àjọ ńlá;èmi yóò máa yìn Ọ́ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.

19 Má ṣe jẹ́ kí àwọn tí ń ṣe ọ̀tá mikí ó yọ̀ lórí ì mi,tàbí àwọn tí ó kórìírá miní àìní dí máa sẹ́jú sí mi.

20 Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tànsí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.

21 Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi;wọ́n sọ wí pé,“Áà! Áà!Ojú wa sì ti rí i.”

22 Ìwọ́ ti ríiÌwọ Olúwa:Má ṣe dákẹ́!Ìwọ Olúwa,Má ṣe jìnnà sí mi!

23 Jí dìde!Ru ara Rẹ̀ sókè fún ààbò mi,fún ìdí mi,Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!

24 Dá mi láre,ìwọ Olúwa,Ọlọ́run mi,gẹ́gẹ́ bí òdodo Rẹ,kí o má sì ṣe jẹ́ kíwọn kí ó yọ̀ lórí mi!

25 Má ṣe jẹ́ kí wọn wínínú ara wọn pé,“Áà! Àti rí ohun tí ọkànwa ń fẹ́:Má ṣe jẹ kí wọn kí ó wí pé,a ti gbé e mì.”

26 Kí ojú kí ó tì wọ́n,lí wọn kí ó sì dààmú pọ̀,tí ń yọ̀ sí ìyọnu mikí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọtí ń gbéraga sí mi.

27 Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mifó fún ayọ̀ àti ìdùnnú,kí wọn máa sọ ọ́ titi lọ,pé gbígbéga ni “Olúwasí àlàáfíà ìránṣẹ Rẹ̀”.

28 Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máasọ̀rọ̀ òdodo Rẹ,àti ìyìn Rẹ ní gbogbo ọjọ́.