1 Ọlọ́run ń ṣàkóso nínú ìpéjọpọ̀ ńlá,ó ṣe ìdájọ́ láàárin àwọn “ọlọ́run òrìṣà”:
2 “Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa gbèjà àwọn aláìsòdodokí ó sì ṣe ojú ìṣájú sí àwọn ènìyàn búburú?
3 Gbèjà àwọn aláìlágbára àti aláìní baba;ṣe ìtọ́jú ẹ̀tọ́ àwọn aláìní àti ẹni ìnilára.
4 Gba àwọn aláìlágbára àti aláìní;gbà wọ́n kùró lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú.
5 “Wọn kò mọ̀ ohunkankan,wọn kò lóye ohunkankan.Wọn ń rìn kiri nínú òkùnkùn;a ni gbogbo ìpínlẹ̀ ayé.
6 “Mo wí pé, ‘Ẹyin ní “Ọlọ́run òrìṣà”;ẹ̀yin ní gbogbo ọmọ ọ̀gá ògo jùlọ.’
7 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin o kú bí ènìyàn lásán;ẹ̀yin ó ṣubú bí ọ̀kan nínú ọmọ aládé.”
8 Dìde Ọlọ́run ṣe ìdájọ́ ayé,nítorí gbogbo orílẹ̀ èdè ni ìní Rẹ.