Sáàmù 73 BMY

ÌWÉ KẸTA

Ẹ̀bẹ̀ Fún Ìdẹra Lọ́wọ́ Aninilára

1 Nítòótọ̀ Ọlọ́run dára fún Ísírẹ́lì,fún àwọn ọlọ́kàn funfun.

2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán;ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.

3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣeféfénígbà tí mo bá rí ọlá àwọn ènìyàn búburú.

4 Wọn kò ṣe wàhálà;ara wọn mókun wọn sì lágbára.

5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ si ènìyàn;a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlomíràn.

6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn;ìwà ìpá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.

7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìsòdodo ti wá;ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdiwọ̀n

8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀ òdì nítiìnilára, wọn ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.

9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀runahọ́n wọn gba ipò ayé.

10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọnwọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀?Ọ̀gá ògo ha ní ìmọ̀ bí?”

12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyíènìyàn asán, wọn ń pọ̀ ní ọrọ̀.

13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́;nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́sẹ̀.

14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu;a sì ń jẹ mí níyà ní gbogbo òwúrọ̀.

15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,”Èmi ó ṣẹ̀sí ìran àwọn ọmọ Rẹ̀.

16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí,O jẹ́ ìnilára fún mi.

17 Tí tí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run;Nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi,

18 Lótítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.

19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìíbí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan!Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọn pátapáta!

20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí,bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa,ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.

21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́àti ọkàn mi sì korò,

22 Mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye;mo jẹ́ ẹranko ní ìwájú Rẹ.

23 Ṣíbẹ̀ mo wà pẹ̀lú Rẹ nígbà gbogbo;ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.

24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn Rẹ tọ́ miní kẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo

25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ?Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn Rẹ.

26 Ara mi àti ọkàn mi leè kùnàṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí miàti ìpín mi títí láé.

27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbéìwọ ti pa gbogbo wọn run;tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ Rẹ

28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́runÈmi ti fi Olúwa Ọlọ́run ṣe ààbò mi;Kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ Rẹ.