1 Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi,nígbà gbogbo ní mo ń ṣàfẹ́rí Rẹóùngbẹ́ Rẹ ń gbẹ ọkàn miara mi fà sí ọ,ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ ti ń ṣàárẹ̀níbi tí kò sí omi
2 Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́mo rí agbára àti ògo Rẹ.
3 Nítorí ìfẹ́ Rẹ dára ju ayé lọ,ètè mi yóò fògo fún ọ.
4 Èmi o yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láàyè,èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ Rẹ.
5 A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ;pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ.
6 Nígbà tí mo rántí Rẹ lórí ìbusùn mi;èmi ń ronú Rẹ títí iṣọ́ òru.
7 Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi,mo kọrin níbi òjijì-ìyẹ́ apá Rẹ.
8 Ọkàn mí fà sí ọ:ọwọ́ ọ̀tún Rẹ gbé mi ró.
9 Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ní a ó parun;wọn o sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìṣàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.
10 Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubúwọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.
11 Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́runẹni tí o fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò sògoṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pa mọ́.