1 Ní ẹ̀bá odò Bábílónì, níbẹ̀ ní àwa gbé jókòóàwa sì sunkún nígbà tí àwa rántí Síónì.
2 Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílóò,tí ó wà láàrin Rẹ̀.
3 Nítorí pé níbẹ̀ ní àwọntí ó kó wa ní ìgbékùn bèèrè orin lọ́wọ́ wá,àti àwọn tí ó ni wá lára bèèrè ìdárayá wí pé;ẹ kọ orin Síónì kan fún wa.
4 Àwa o ti ṣe kọ orin Olúwa ni ilẹ̀ àjèjì
5 Jérúsálẹ́mù, bí èmi bá gbàgbé Rẹjẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò Rẹ.
6 Bí èmi kò bá rántí Rẹ,jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi;bí èmi kò bá fi Jérúsálẹ́mù ṣáájúolórí ayọ̀ mi gbogbo.
7 Olúwa rántí ọjọ́ Jérúsálẹ́mù,lára àwọn ọmọ Édómù,àwọn ẹni tí ń wí pé,wó o palẹ̀, wó o palẹ̀ de ìpílẹ̀ Rẹ̀!
8 Ìwọ, ọmọbìnrin Bábílónì, ẹni tí a o parun;ìbùkún ní fún ẹni tí ó san án fúnọ bí ìwọ ti rò sí wa.
9 Ìbùkún ní fún ẹni tí ó mú tí ó sì fiọmọ wẹ́wẹ́ Rẹ̀ ṣán òkúta.