27 Wọ́n ń ta gbọ̀n-ọ́ngbọ̀n-ọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn:ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókèsí Olúwa nínú ìdàámú wọn,ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́-rọ́rọ́bẹ́ẹ̀ ní rirú omi Rẹ̀ duro jẹ́ẹ́;
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀,ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ,
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ Rẹ̀àti iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárin àwọn ènìyànkí wọn kí ó sì yín ín ní ìjọ àwọn àgbà.
33 Ó sọ odò di ihà,àti orisun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.