1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi;ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Nítorí ó yí etí Rẹ̀ padà sí mi,èmi yóò máa, pè é ní wọ̀n ìgbà tí mo wà láàyé.
3 Òkun ikú yí mi ka,ìrora isà òkú wá sórí mi;ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi.
4 Nígbà náà ni mo ké pé orúkọ Olúwa:“Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi”