32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ Rẹ,nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
33 kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ Rẹ;nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin Rẹ mọ́èmi yóò sì máa kíyèsíi pẹ̀lú ọkàn mi.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ Rẹ hàn mí,nítorí nínú Rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin Rẹ̀kí ó má ṣe sí ojú kòkòrò mọ́.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán:pa ayé mí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Rẹ.
38 Mú ìlérí Rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ Rẹ,nítorí òfin Rẹ dára.