8 Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀;bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú,kíyèsí i, ìwọ wà níbẹ̀.
9 Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀,kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin òkun;
10 Àní níbẹ̀ náà ni ọwọ́ Rẹ̀ yóò fà míọwọ́ ọ̀tún Rẹ yóò sì dì mí mú.
11 Bí mo bá wí pé, ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀;kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.
12 Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọdọ̀ Rẹ;ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán;àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjìbákan náà ní fún ọ.
13 Nítorí ìwọ ní ó dá ọkàn mi;ìwọ ní ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.
14 Èmi yóò yìn ọ nítorí tẹ̀rùtẹ̀rù àtitìyanu tìyanu ní a dá mi;ìyanu ní isẹ́ Rẹ; èyí nì níọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú