2 Òun ni Ọlọ́run ìfẹ́ mi àti odi alágbára mi,ibi gíga mi àti olùgbàlà mi, asà mi,ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé,ẹni tí ó tẹ́rí àwọn ènìyàn ba lábẹ́ mi
3 Olúwa, kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣàníyàn fún-ún,tàbi ọmọ ènìyàn tí ìwọ fi ń ronú nípa Rẹ̀?
4 Ènìyàn rí bí èmi;ọjọ́ Rẹ̀ rí bí òjìji tí ń kọjá lọ.
5 Tẹ ọ̀run Rẹ ba, Olúwa, kí o sì sọ̀kalẹ̀;tọ́ àwọn òkè ńlá wọn yóò sí, rú èéfín.
6 Rán mọ̀nàmọ́ná kí ó sì fọ́n àwọn ọ̀ta ká;ta ọfà Rẹ kí ó sì dà wọ́n rú.
7 Na ọwọ́ Rẹ sílẹ̀ láti ibi gíga;gbà mí kí ó sì yọ mí nínú ewukúrò nínú omi ńlá:kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì.
8 Ẹnu ẹni tí ó kún fún èkéẹni tí ọwọ́ ọ̀tún Rẹ̀ jẹ́ ìrẹ́jẹ.