1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa nítorí ohun rereláti máa kọrin ìyìnsí Ọlọ́run wa,ó yẹ láti kọrin ìyìn síi.
2 Olúwa kọ́ Jérúsálẹ́mù;O ko àwọn Ísírẹ́lì tí a lé sọnù jọ.
3 Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bajẹ́ sànó sì di ọgbẹ́ wọn.
4 Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ó sì pe ọ̀kọ̀ọkan wọn ní orúkọ
5 Títóbi ní Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbáraòye Rẹ̀ kò sì ní òpin.
6 Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀bẹ́ẹ̀ ni ó Rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.