1 Èéṣe tí àwọn orílẹ̀ èdè fi ń dìtẹ̀,àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkísí asán?
2 Àwọn ọba ayé péjọ pọ̀àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀sí Olúwaàti sí Ẹni àmì òróró Rẹ̀.
3 Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já,”“kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
4 Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
5 Nígbà náà ni ó bá wọn wí ní ìbínú Rẹ̀ó sì dẹ́rùba bà wọ́n ní ìrunú Rẹ̀, ó wí pé,
6 “Èmi ti fi ọba mi sí ipòlórí Síónì, òkè mímọ́ mi.”