5 Nígbà náà ni ó bá wọn wí ní ìbínú Rẹ̀ó sì dẹ́rùba bà wọ́n ní ìrunú Rẹ̀, ó wí pé,
6 “Èmi ti fi ọba mi sí ipòlórí Síónì, òkè mímọ́ mi.”
7 Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa:Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi;lónìí, èmi ti di baba Rẹ.
8 Béèrè lọ́wọ́ mi,Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀ èdè di ìní Rẹ,òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún Rẹ.
9 Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọnìwọ yóò sì rún wọn wómú wómú bí ìkòkò amọ̀”.
10 Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọgbọ́n;ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
11 Ẹ ṣin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rùẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.