2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn Rẹ̀ fún un,bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu Rẹ̀. Sela
3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nàìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
4 O ní ọwọ́ Rẹ, ìwọ sì fi fún un,àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
5 Ògo Rẹ̀ pọ̀ nípaṣẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún-un;ìwọ́ sì jẹ́ kí iyì ọlánlá Rẹ̀ wà lára Rẹ.
6 Dájúdájú ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún-un:ìwọ́ sì mú inú Rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u Rẹ̀.
7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa;nípaṣẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá ògo tí kì í kùnàkì yóò sípò padà.
8 Ọwọ́ Rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀ta a Rẹ rí;ọwọ́ ọ̀tún Rẹ yóò wà àwọn tí o kóríra Rẹ rí.