5 Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà;ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójú tì wọ́n.
6 Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́ kì í sì í ṣe ènìyàn;mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn ẹlẹ́yà àwọ́n ènìyàn
7 Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà;wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí i wọn pé.
8 “Ó gbẹkẹ Rẹ̀ lé Olúwa;jẹ́ kí Olúwa gbà á là.Jẹ́ kí ó gbà a là,nítorí pé ó ni ayọ̀ nínú Rẹ̀.”
9 Ṣíbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú;ìwọ ni ó mú mi wà láìléwunígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
10 Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wánígbà tí ìyá a mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi
11 Má ṣe jìnnà sími,nítorí pé ìyọnu sún mọ́ tòsíkò sì sí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.