11 Nítorí orúkọ Rẹ̀, áà! Olúwa,dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jìn mí, nítorí tí ó tóbi.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa?Yóò kọ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà,àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u Rẹ̀;ó sọ májẹ̀mú Rẹ̀ di mímọ̀ fún wọn.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa,nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
16 Yípadà sími, kí o sì ṣe oore fún mi;nítorí pé mo nìkàn wà, mo sì di olùpọ́njú.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi;kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú ù mi.