10 Àyà mi ń mí hẹlẹ,agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni,ó ti lọ kúrò lára mi.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ miàti àwọn ẹlẹgbẹ́ midúró lókèèrè rérékúrò níbi ìpọ́njú mi,àwọn alábàágbé é mi,dúró lókèèrè.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí midẹ okùn sílẹ̀ fún mi;àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lárań sọ̀rọ̀ nípa ìparun,wọ́n sì ń gbérò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi,èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀;àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
14 Ní tòótọ́,mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́ràn,àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa,ìwọ ni mo dúró dè;ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi,ẹni tí yóò dáhùn.
16 Nítorí tí mo gbàdúrà,“Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí;nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi”.