6 Ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run;apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyànni Olúwa yóò kórìíra.
7 Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú Rẹ̀,èmi yóò wá sínú ilé Rẹ̀;ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríbasí ìhà tẹ́ḿpìlì mímọ́ Rẹ̀.
8 Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo Rẹ,nítorí àwọn ọ̀ta mi,mú ọ̀nà Rẹ tọ́ níwájú mi.
9 Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́;ọkàn wọn kún fún ìparun.ọ̀nà ọ̀fun wọn ni iṣà òkú tí ó sí sílẹ̀;pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.
10 Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run!Jẹ́ kí rìkísí wọn jẹ́ ìṣubú wọn.Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn,nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
11 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀;jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí.Tan ààbò Rẹ sórí wọn,àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ Rẹ yóò máa yọ̀ nínú Rẹ.
12 Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo;ìwọ fi ojú rere Rẹ yí wọn ká bí àṣà.