10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, Dan wa wò;ìwọ dán wa bí a tí ń Dan fàdákà wo
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀no sì di ẹ̀rù lé ẹ̀yìn wa
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gun wá ní oríàwa la iná àti omi kọjáṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
13 Èmi ó wá sí tẹ́ḿpìlì Rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísunkí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ
14 Ẹ̀jẹ́ ti ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọnígbà tí mo wà nínú ìsòro.
15 Èmi o sun ẹbọ ọlọ́ràá sí ọàti ẹbọ ọ̀rá àgbò;èmi o rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. Sela
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa;ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.