5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe,Iṣẹ́ Rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
6 O yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ,wọ́n fi ẹsẹ̀ rìn inú omi kọjá,níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú Rẹ.
7 O ń jọba títí láé nípa agbára Rẹ̀,ojú Rẹ̀ ń wò orílẹ̀ èdèkí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. Sela
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn,jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohun ìyìn Rẹ̀;
9 O ti dá ààbò bo ẹ̀mí wakò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí o yẹ̀
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, Dan wa wò;ìwọ dán wa bí a tí ń Dan fàdákà wo
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀no sì di ẹ̀rù lé ẹ̀yìn wa