2 Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ,kí ó fẹ́ wọn lọ;bí ìdà tí i yọ́ níwájú iná,kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
3 Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùnkí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run;kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
4 Ẹ kọrin sí Ọlọ́run,ẹ kọrin ìyìn síi,ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń ré kọjá ní ihà.JAH ni orúkọ Rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Rẹ̀.
5 Baba àwọn aláìní baba àti Onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ni ibùgbéRẹ̀ mímọ́
6 Ọlọ́run gbé ẹni òfokálẹ̀ nínú ìdílé,ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orinṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
7 Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn Rẹ̀, Ọlọ́run,tí ń kọjá lọ láàrin ihà, Sela
8 Ilẹ̀ mi títí,àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde,níwájú Ọlọ́run,ẹni Sínáì,níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Ísírẹ́lì.