24 Tú ìbínú Rẹ jáde sí wọn;kí ìbínú gbígbóná Rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Kí ibùjókòó wọn di ahoro;kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù,àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe
27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn;Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà Rẹ.
28 Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyèkí á má kà wọn pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Ṣùgbọ́n talákà àti ẹni-ìkáánú ni èmí,Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà Rẹ gbé mi lékè.
30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run gaèmi yóò fí ọpẹ́ gbé orúkọ Rẹ̀ ga.