16 Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run,nígbà tí àwọn omi rí ọ,ẹ̀rù bà wọ́n,nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
17 Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀,àwọ̀sánmọ̀ fí àrá dáhùn;ọfà Rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú
18 Àrá Rẹ̀ ni a gbọ ní ibi ìjì,ìmọ́lẹ̀ Rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé;ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
19 Ìpa Rẹ̀ gba òkun, ọ̀nà Rẹ ń bẹ nínú òkun,Ọ̀nà la omi alágbára kọ́já ipa Rẹ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá,nítòótọ́ a kò rí ojú ẹṣẹ̀ Rẹ̀.
20 Ó tọ́ àwọn ènìyàn Rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹrannípa ọwọ́ Mósè àti Árónì.