9 Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú?Ní ìbínú Rẹ̀, ó ha sé ojú rere Rẹ̀ mọ́? Sela
10 Èmí wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi,pé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
11 Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa:bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
12 Èmi ṣàṣárò lórí iṣẹ́ Rẹ gbogbopẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára Rẹ.
13 Ọlọ́run, Ọ̀nà Rẹ jẹ́ mímọ́.Ọlọ́run wo ní ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
14 Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu;ìwọ fi agbára Rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
15 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára Rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà,àwọn ọmọ Jákọ́bù àti Jósẹ́fù. Sela