47 Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ó bá èso sìkàmore wọn jẹ́
48 Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyínagbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná
49 Ó mú kíkorò ìbínú Rẹ̀ wá sí wọn lára,ìrunú àti ikáánú, àti ìpọ́njú,nípa rírán ańgẹ́lì apanirun sí wọn.
50 Ó pèṣè ipa fún ìbínú Rẹ̀òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikúṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-àrùn
51 Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin ÉjíbítìOlórí agbára wọn nínú àgọ́ Ámù
52 Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn Rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran;ó sọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú ihà.
53 Ó dáàbòbò wọ́n dáadáa, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́nṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.