54 Bákan náà ní ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ Rẹòkè tí ọwọ́ ọ̀tún Rẹ̀ tí gbà
55 Ó lé orílẹ̀ èdè jáde níwájú wọnó sì pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní;ó mú àwọn ẹ̀yà Íṣírẹ́lì jókòó ní ilẹ̀ wọn.
56 Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wòwọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá Ògo;wọn kò pa àṣẹ Rẹ̀ mọ́.
57 Gẹ́gẹ́ bí baba wọn, wọn jẹ́ aláìsòdodo gẹ́gẹ́ bi ọrun ẹ̀tàn
58 Wọ́n bí nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn;wọn rú owú Rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn
59 Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn,inú bí i gidigidi;ó kọ Ísírẹ́lì pátapáta.
60 Ó kọ àgọ́ Ṣílò sílẹ̀,àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrin àwọn ènìyàn.