63 Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn,àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
64 A fi àlùfáà wọn fún idà,àwọn opó wọn kò sì le è sunkún.
65 Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun,gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jù kúrò nínú ìraníyè ọtí.
66 Ó kọlu àwọn ọta Rẹ̀ padà;ó fí wọn sínú ìtìjú ayérayé.
67 Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Jósẹ́fù,kò sì yan ẹ̀yà Éfúráímù;
68 Ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Júdà,òkè Síónì, èyí tí ó fẹ́ràn.
69 Ó kọ́ ibi mímọ́ Rẹ̀, ibí gíga,gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí Rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.