15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo,àti gbogbo àwọn ọlọ́kàndídúró ṣinṣin yóò tẹ̀ lé e lẹ́yìn.
16 Ta ni yóò dìde fún misí àwọn olùṣe búburú?Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́,èmi fẹ́rẹ̀ má a gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́
18 Nígbà tí mo sọ pé “ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ Rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi,ìtùnú Rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú Rẹẹni tí ń fí òfin dìmọ̀ ìwà ìkà?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ si olódodowọ́n sì ń dá àwọn aláìsẹ̀ lẹ́bi sí ikú.