2 Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí miláti jẹ ẹran ara mi,àní àwọn ọ̀ta mi àti àwọn abínúkú ù mi,wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
3 Bí ọmọ ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi,ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù;bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi,nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
4 Ohun kan ni mo bèèrè nípasẹ̀ Olúwa,òun ni èmi yóò máa wá kiri:kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwaní ọjọ́ ayé mi gbogbo,kí èmi: kí ó le kíyèsí ẹwà Olúwa,kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹ́ḿpìlì Rẹ.
5 Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njúòun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ Rẹ̀;níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ Rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́;yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
6 Ní ìsinsin yìí a ti gbé orí mi sókèga ju ti àwọn ọ̀tá a mi lọ tí ó yí mí ká;èmi yóò rúbọ nínú àgọ́ Rẹ ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀;èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
7 Gbọ́ ohùn mi nígbà tẹ́mi báà ń pè, Áà Olúwa,ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn;
8 “Wá,” ọkàn mi wí pé, “wá ojú u Rẹ̀”Ojú ù Rẹ, Olúwa, ni èmí ń wá,