3 Nígbà tí mo dákẹ́,egungun mi di gbígbó dànùnípa ìkérora mi ní gbogbo ọjọ́.
4 Nítorí pé ni ọ̀sán àti ní òruọwọ́ Rẹ̀ wúwo sími lára;agbára mi gbẹ tángẹ́gẹ́ bí ooru ẹ̀ẹ̀rùn Sela
5 Èmi jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọàti pé èmi kò sì fi àìsòdodo mi pamọ́.Èmi wí pé, “Èmi yóò jẹ́wọ́ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Olúwa,”ìwọ sì dáríẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jìn mí. Sela
6 Nítorí náà jẹ́ kí gbogbo àwọn olódodo máa gbà àdúrà sí ọní ìgbà tí a le ri ọ;nitòótọ́ nígbà tí ìṣàn omi ńlá bá ru sókè,wọn kì yóò le dé ọ̀dọ̀ Rẹ̀.
7 Ìwọ ni ibi ìpamọ́ mi;ìwọ yóò pa mí mọ́ kúrò nínú ìyọnu;ìwọ yóò fi orin ìgbàlà yí mi ka. Sela
8 Èmi yóò kọ́ ọ, èmi yóò sì fi ẹsẹ̀ Rẹ lé ọ̀nà ìwọ yóò rìnèmi yóò máa gbà ọ ní ìyànjú, èmi yóò sì máa fi ojú mi tọ́ ọ.
9 Má ṣe dàbí ẹsin tàbí ìbaka,tí kò ní òyeẹnu ẹni tí a gbọdọ̀ fi ìjánu bọ̀,kí wọn má ba à sún mọ́ ọ.