1 OlúwaMá ṣe bá mi wí nínú ìbínú Rẹ,bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mínínú ìrunú Rẹ̀.
2 Nítorí tí ọfà Rẹkàn mọ́ mi ṣinṣin,ọwọ́ Rẹ sìkì mí mọ́lẹ̀.
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à minítorí ìbínú Rẹ;kò sí àlàáfíà nínú egungun minítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
4 Nítorí àìṣedédé miti borí mi mọ́lẹ̀;wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgàtí ó wúwo jù fún mi:
5 Ọgbẹ́ mi ń rùnó sì díbàjẹ́nítorí òmùgọ̀ mi;
6 Èmi ń jòwèrè:orí mi tẹ̀ ba gidigidièmi ń sọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.