1 Bí àgbọ̀nrín tí ń mí hẹlẹ sí ìpa odò omi,bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi n mì hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run
2 Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè.Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?
3 Oúnjẹ mi ní omijé miní ọ̀sán àti ní òru,nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́,“Ọlọ́run Rẹ̀ dà?”
4 Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí,èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi:èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ,èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́runpẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn,pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.
5 Èéṣe tí o fi n rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?Èéṣe tí ara Rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?Ìwọ ṣe ìrètí ni ti Ọlọ́run,nítorí èmi yóò sáà máa yìn ín.
6 Olùgbàlà mi àtiỌlọ́run mi,ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi:nítorí náà, èmi ó rántí Rẹláti ilẹ̀ Jọ́dánì wá,láti Hámónì láti òkè Mísárì.
7 Ibú omi ń pe ibú ominípa híhó omi ṣíṣàn Rẹ̀gbogbo rírú omi àti bíbì omi Rẹ̀bò mí mọ́lẹ̀.