7 Ibú omi ń pe ibú ominípa híhó omi ṣíṣàn Rẹ̀gbogbo rírú omi àti bíbì omi Rẹ̀bò mí mọ́lẹ̀.
8 Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ Rẹ̀,àti ni àṣálẹ́ ni orin Rẹ̀ wà pẹ̀lú miàdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.
9 Èmi wí fún Ọlọ́run àpátà mi,“Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi?Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́,nítorí ìnilára ọ̀ta?”
10 Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tíàwọn ọ̀ta mi ń gàn mí,Bí wọn ti ń béèrè ni gbogbo ọjọ́.“Níbo ni Ọlọ́run Rẹ wà?”
11 Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?Èéṣe tí ara Rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?Fi ìrètí Rẹ sínú Ọlọ́run,nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun niOlùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.