10 Nígbà tí mo sunkúntí mo sì ń fi ààwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyàèyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà,àwọn ènìyàn ń pòwe mọ́ mi.
12 Àwọn tí ó jòkòó ní ẹnu ibodè ń bú mi,mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi niìwọ ni èmi n gbàdúrà mi sí Olúwa,ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbàỌlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi Rẹ,dá mí lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà Rẹ tí ó dájú.
14 Gbá mí kúrò nínú ẹrẹ̀,Má ṣe jẹ́ kí ń rí;gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí o korìíra mi,kúrò nínú ibú omi.
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mìkí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu Rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Dá mí lóhùn, Olúwa nínú ìṣeun ìfẹ́ Rẹ;nínú ọ̀pọ̀ àánú Rẹ yípadà sí mi.