13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi niìwọ ni èmi n gbàdúrà mi sí Olúwa,ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbàỌlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi Rẹ,dá mí lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà Rẹ tí ó dájú.
14 Gbá mí kúrò nínú ẹrẹ̀,Má ṣe jẹ́ kí ń rí;gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí o korìíra mi,kúrò nínú ibú omi.
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mìkí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu Rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Dá mí lóhùn, Olúwa nínú ìṣeun ìfẹ́ Rẹ;nínú ọ̀pọ̀ àánú Rẹ yípadà sí mi.
17 Má ṣe pa ojú Rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ Rẹ:yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Súnmọ́ tòsí kí ó sì gbà mí là;rà mí padà nítorí àwọn ọ̀ta mi.
19 Ìwọ tí mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá;Gbogbo àwọn ọ̀ta mi wà níwájú Rẹ̀.