1 Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, Olúwa,kíyèsí àròyé mi.
2 Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́,ọba mi àti Ọlọ́run mi,nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.
3 Ní òwúrọ̀, Olúwa, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi;ní òwúrọ̀ èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú Rẹ̀èmi yóò sì dúró ní ìrètí.
4 Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú;bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.
5 Àwọn agbéraga kò le è dúró níwájú Rẹ̀;ìwọ kóríra gbogbo àwọn aṣebi.